Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 21:12-23 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Wọ́n gbéra láti ibẹ̀, wọ́n lọ pa àgọ́ sí àfonífojì Seredi.

13. Wọ́n tún ṣí kúrò ní àfonífojì Seredi, wọ́n pa àgọ́ wọn sí òdìkejì odò Arinoni, tí ó wà ní aṣálẹ̀ tí ó bẹ̀rẹ̀ láti agbègbè àwọn ará Amori. Odò Arinoni jẹ́ ààlà ilẹ̀ Moabu, ó wà láàrin ilẹ̀ Moabu ati ilẹ̀ Amori.

14. Nítorí náà ni a ṣe kọ ọ́ sinu Ìwé Ogun OLUWA pé:“Ìlú Wahebu ní agbègbè Sufa,ati àwọn àfonífojì Arinoni,

15. ati ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àwọn àfonífojì náàtí ó lọ títí dé ìlú Ari,tí ó lọ dé ààlà Moabu.”

16. Láti ibẹ̀, wọ́n ṣí lọ sí Beeri, níbi kànga tí ó wà níbẹ̀ ni OLUWA ti sọ fún Mose pé, “Pe àwọn eniyan náà jọ, n óo sì fún wọn ní omi.”

17. Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli kọ orin yìí pe:“Ẹ sun omi jáde, ẹ̀yin kànga!Ẹ máa kọrin sí i!

18. Kànga tí àwọn ọmọ aládé gbẹ́,tí àwọn olórí wàpẹlu ọ̀pá àṣẹ ọba ati ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀ wọn.”Wọ́n sì ṣí kúrò níbẹ̀ lọ sí aṣálẹ̀ Matana.

19. Láti Matana, wọ́n ṣí lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli wọ́n ṣí lọ sí Bamotu,

20. láti Bamotu wọ́n ṣí lọ sí àfonífojì tí ó wà ní ilẹ̀ àwọn Moabu ní ìsàlẹ̀ òkè Pisiga tí ó kọjú sí aṣálẹ̀.

21. Àwọn ọmọ Israẹli bá ranṣẹ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori pé,

22. “Jọ̀wọ́, gbà wá láàyè láti gba orí ilẹ̀ rẹ kọjá. Àwa ati àwọn ẹran ọ̀sìn wa kò ní yà kúrò ní ojú ọ̀nà wọ inú oko yín, tabi ọgbà àjàrà yín. Bẹ́ẹ̀ ni a kò ní mu omi kànga yín. Ojú ọ̀nà ọba ni a óo máa rìn títí a óo fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”

23. Sihoni kò gbà kí àwọn ọmọ Israẹli gba orí ilẹ̀ rẹ̀ kọjá. Ṣugbọn ó kó àwọn ọmọ ogun rẹ̀, wọ́n sì bá àwọn ọmọ Israẹli jagun ní Jahasi ninu aṣálẹ̀.

Ka pipe ipin Nọmba 21