Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mika 4:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà tí ó bá yá, a óo fìdí òkè ilé OLUWA múlẹ̀bí òkè tí ó ga jùlọ,a óo gbé e ga ju àwọn òkè yòókù lọ,àwọn eniyan yóo sì máa wọ́ wá sibẹ.

2. Ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè yóo wá, wọn yóo sì wí pé,“Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á lọ sórí òkè OLUWA,ẹ jẹ́ kí á lọ sí ilé Ọlọrun Jakọbu,kí ó lè kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀,kí á sì lè máa tọ̀ ọ́.”Nítorí pé láti Sioni ni òfin yóo ti máa jáde,ọ̀rọ̀ OLUWA yóo sì máa jáde láti Jerusalẹmu.

3. Yóo ṣe ìdájọ́ láàrin ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè,ati láàrin àwọn orílẹ̀-èdè tí ó lágbára ní ọ̀nà jíjìn réré;wọn yóo fi idà wọn rọ ọkọ́,wọn yóo sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé;àwọn orílẹ̀-èdè kò ní yọ idà sí ara wọn mọ́,wọn kò sì ní kọ́ ogun jíjà mọ́.

4. Ṣugbọn olukuluku yóo jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀,ati lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀, kò sì ní sí ẹni tí yóo dẹ́rùbà wọ́n;nítorí pé OLUWA àwọn ọmọ ogun ni ó sọ bẹ́ẹ̀.

5. Olukuluku orílẹ̀-èdè a máa rìn ní ọ̀nà tí oriṣa rẹ̀ là sílẹ̀, ṣugbọn ọ̀nà OLUWA tí Ọlọrun wa là sílẹ̀ ni àwa yóo máa tọ̀ títí laelae.

6. OLUWA ní, “Nígbà tí ó bá yá, n óo kó gbogbo àwọn arọ jọ, n óo kó àwọn tí mo ti túká jọ, ati àwọn tí mo ti pọ́n lójú.

Ka pipe ipin Mika 4