Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lefitiku 26:43-46 BIBELI MIMỌ (BM)

43. Ṣugbọn wọn yóo jáde kúrò ninu ilẹ̀ náà, ilẹ̀ náà yóo sì ní ìsinmi nígbà ti ó bá wà ní ahoro, nígbà tí wọn kò bá sí níbẹ̀. Wọ́n gbọdọ̀ gba ìjẹníyà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé, wọ́n kẹ́gàn ìdájọ́ mi, wọ́n sì kórìíra ìlànà mi.

44. Sibẹsibẹ nígbà tí wọ́n bá wà ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, n kò ní ṣàì náání wọn; bẹ́ẹ̀ ni n kò ní kórìíra wọn débi pé kí n pa wọ́n run patapata, kí n sì yẹ majẹmu mi pẹlu wọn, nítorí èmi ni OLUWA Ọlọrun wọn.

45. Ṣugbọn n óo tìtorí tiwọn ranti majẹmu tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, àní àwọn tí mo kó jáde láti ilẹ̀ Ijipti lójú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè, kí n lè jẹ́ Ọlọrun wọn. Èmi ni OLUWA.”

46. Àwọn ni ìlànà ati òfin tí OLUWA fi lélẹ̀ láàrin òun ati àwọn ọmọ Israẹli, láti ọwọ́ Mose.

Ka pipe ipin Lefitiku 26