Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Kinni 6:13-32 BIBELI MIMỌ (BM)

13. Ṣalumu ni baba Hilikaya; Hilikaya bí Asaraya,

14. Asaraya bí Seraaya; Seraaya sì bí Jehosadaki.

15. Jehosadaki lọ sí ìgbèkùn nígbà tí Ọlọrun jẹ́ kí Nebukadinesari wá kó Juda ati Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.

16. Àwọn ọmọ Lefi ni: Geriṣoni, Kohati ati Merari.

17. Àwọn ọmọ Geriṣoni ni: Libini ati Ṣimei.

18. Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Iṣari, Heburoni, ati Usieli.

19. Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili ati Muṣi. Àwọn ni baba ńlá àwọn ọmọ Lefi.

20. Àwọn tí wọ́n ṣẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Geriṣoni nìwọ̀nyí: Libini ni baba Jahati, Jahati bí Sima,

21. Sima bí Joa, Joa bí Ido, Ido bí Sera, Sera sì bí, Jeaterai.

22. Àwọn tí ó ṣẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Kohati nìwọ̀nyí: Aminadabu ni baba Kora, Kora ló bí Asiri;

23. Asiri bí Elikana, Elikana bí Ebiasafu, Ebiasafu sì bí Asiri.

24. Asiri ni baba Tahati, Tahati ló bí Urieli, Urieli bí Usaya, Usaya sì bí Saulu.

25. Ọmọ meji ni Elikana bí: Amasai ati Ahimotu.

26. Àwọn ọmọ Ahimotu nìwọ̀nyí: Elikana ni baba Sofai, Sofai ni ó bí Nahati;

27. Nahati bí Eliabu, Eliabu bí Jerohamu, Jerohamu sì bí Elikana.

28. Samuẹli bí ọmọkunrin meji: Joẹli ni àkọ́bí, Abija sì ni ikeji.

29. Àwọn ọmọ Merari nìwọ̀nyí: Mahili ni baba Libini, Libini bí Ṣimei,

30. Ṣimei bí Usali, Usali bí Ṣimea, Ṣimea bí Hagaya, Hagaya sì bí Asaya.

31. Dafidi fi àwọn wọnyi ṣe alákòóso ẹgbẹ́ akọrin ninu ilé OLUWA lẹ́yìn tí wọn ti gbé Àpótí Majẹmu OLUWA sibẹ;

32. àwọn ni wọ́n ń kọ orin ninu Àgọ́ Àjọ títí tí Solomoni fi kọ́ ilé OLUWA parí ní Jerusalẹmu; àṣegbà ni wọ́n ń ṣiṣẹ́ wọn.

Ka pipe ipin Kronika Kinni 6