Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Kinni 4:12-21 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Eṣitoni yìí ni ó bí Betirafa, Pasea ati Tẹhina. Tẹhina sì ni baba Irinahaṣi. Àwọn ni wọ́n ń gbé Reka.

13. Kenasi bí ọmọ meji: Otinieli ati Seraaya. Otinieli náà bí Hatati ati Meonotai.

14. Meonotai ni baba Ofira.Seraaya sì ni baba Joabu, baba àwọn ará Geharaṣimu, ìlú àwọn oníṣọ̀nà. Àwọn ni wọ́n tẹ gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ àwọn oníṣẹ́ ọwọ́ dó.

15. Kalebu, ọmọ Jefune, bí ọmọ mẹta: Iru, Ela, ati Naamu. Ela ni ó bí Kenasi.

16. Jehaleli sì ni baba Sifi, Sifa, Tiria, ati Asareli.

17. Ẹsira bí Jeteri, Meredi, Eferi, ati Jaloni. Meredi fẹ́ Bitia, ọmọbinrin Farao. Wọ́n bí ọmọbinrin kan tí ń jẹ́ Miriamu ati ọmọkunrin meji: Ṣamai ati Iṣiba.

18. Iṣiba ni baba Eṣitemoa. Meredi tún ní iyawo mìíràn, òun jẹ́ ará Juda, ó bí ọmọkunrin mẹta fún un: Jeredi, baba Gedori, Heberi baba Soko, ati Jekutieli, baba Sanoa.

19. Hodia fẹ́ arabinrin Nahamu, àwọn ọmọ wọn ni wọ́n ṣẹ ẹ̀yà Garimi, tí wọn ń gbé ìlú Keila sílẹ̀, ati àwọn ìran Maakati tí wọn ń gbé ìlú Eṣitemoa.

20. Simoni ni baba Aminoni, Rina, Benhanani ati Tiloni. Iṣi sì ni baba Soheti ati Benisoheti.

21. Ṣela, ọ̀kan ninu àwọn ọmọ Juda, ni baba Eri, baba Leka. Laada ni baba Mareṣa, ati ìdílé àwọn tí wọ́n ń hun aṣọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ funfun ní Beti Aṣibea

Ka pipe ipin Kronika Kinni 4