Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Kinni 16:8-20 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ẹ fi ọpẹ́ fún OLUWA, ẹ képe orúkọ rẹ̀,ẹ kéde ohun tí ó ti ṣe fún àwọn orílẹ̀-èdè.

9. Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn sí i,ẹ sọ nípa àwọn ohun ìyanu tí ó ṣe!

10. Ẹ máa fi orúkọ rẹ̀ ṣògo,kí ọkàn àwọn tí wọn ń sin OLUWA kún fún ayọ̀.

11. OLUWA ni kí ẹ máa tọ̀ lọ fún ìrànlọ́wọ́,Ẹ máa sìn ín nígbà gbogbo.

12. Ẹ ranti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀,gbogbo nǹkan ìyanu tí ó ṣe, ati gbogbo ìdájọ́ rẹ̀,

13. ẹ̀yin ọmọ Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀,ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.

14. Òun ni OLUWA Ọlọrun wa,ìdájọ́ rẹ̀ ká gbogbo ayé.

15. Kò ní í gbàgbé majẹmu rẹ̀ títí lae,àní àwọn ohun tí ó ti pa láṣẹ láti ṣe fún ẹgbẹẹgbẹrun ìran,

16. majẹmu tí ó bá Abrahamu dá,ìlérí tí ó ti ṣe fún Isaaki,

17. tí ó sì ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pẹlu Jakọbu,gẹ́gẹ́ bíi majẹmu ohun tí yóo wà títí lae,

18. ó ní, “Ẹ̀yin ni n óo fún ní ilẹ̀ Kenaani,bí ohun ìní yín, tí ẹ óo jogún.”

19. Nígbà tí wọn kò tíì pọ̀ pupọ,tí wọn kò sì jẹ́ nǹkan,tí wọ́n jẹ́ àjèjì níbẹ̀,

20. tí wọn ń lọ káàkiri láti orílẹ̀-èdè kan dé ekeji,láti ìjọba kan sí òmíràn,

Ka pipe ipin Kronika Kinni 16