Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Kinni 11:2-7 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Látẹ̀yìnwá, nígbà tí Saulu pàápàá wà lórí oyè, ìwọ ni ò ń ṣáájú Israẹli lójú ogun. OLUWA Ọlọrun rẹ sì ti ṣèlérí fún ọ pé ìwọ ni o óo máa ṣe olùṣọ́ àwọn ọmọ Israẹli, eniyan òun, tí o óo sì jọba lé wọn lórí.”

3. Nítorí náà, àwọn àgbààgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ Dafidi ọba, ní Heburoni. Dafidi sì bá wọn dá majẹmu níbẹ̀ níwájú OLUWA. Wọ́n fi òróró yàn án ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ OLUWA láti ẹnu Samuẹli.

4. Dafidi ati àwọn ọmọ Israẹli lọ gbógun ti ìlú Jerusalẹmu, (Jebusi ni orúkọ Jerusalẹmu nígbà náà, ibẹ̀ ni àwọn ará Jebusi ń gbé.)

5. Àwọn ará Jebusi sọ fún Dafidi pé, “O ò ní wọ ìlú yìí.” Ṣugbọn Dafidi ṣẹgun ibi ààbò Sioni, tí à ń pè ní ìlú Dafidi.

6. Dafidi ní, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ́kọ́ pa ará Jebusi kan ni yóo jẹ́ balogun fún àwọn ọmọ ogun mi.” Joabu, ọmọ Seruaya ni ó kọ́kọ́ lọ, ó sì di balogun.

7. Dafidi lọ ń gbé ibi ààbò náà, nítorí náà ni wọ́n ṣe ń pe ibẹ̀ ní ìlú Dafidi.

Ka pipe ipin Kronika Kinni 11