Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Keji 9:1-3 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà tí ọbabinrin ìlú Ṣeba gbọ́ nípa òkìkí Solomoni, ó wá sí Jerusalẹmu láti wá dán an wò pẹlu àwọn ìbéèrè tó le. Ó wá ninu ọlá ńlá rẹ̀. Ọ̀pọ̀ eniyan ni wọ́n tẹ̀lé e lẹ́yìn, pẹlu àwọn ràkúnmí tí wọ́n ru oríṣìírìṣìí turari olóòórùn dídùn, ati ọpọlọpọ wúrà ati òkúta olówó iyebíye. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Solomoni, ó sọ gbogbo ohun tí ó wà lọ́kàn rẹ̀ fún un.

2. Solomoni dáhùn gbogbo ìbéèrè rẹ̀. Kò sí ẹyọ kan tí ó rú Solomoni lójú, tí kò dáhùn pẹlu àlàyé.

3. Nígbà tí ọbabinrin Ṣeba rí i bí ọgbọ́n Solomoni ti jinlẹ̀ tó, ati ààfin tí ó kọ́,

Ka pipe ipin Kronika Keji 9