Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Keji 26:4-7 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ó ṣe nǹkan tí ó tọ́ níwájú OLUWA, bí Amasaya baba rẹ̀.

5. Ó sin Ọlọrun nígbà ayé Sakaraya, nítorí pé Sakaraya ń kọ́ ọ ní ìbẹ̀rù Ọlọrun. Ní gbogbo àkókò tí ó fi ń sin Ọlọrun, Ọlọrun bukun un.

6. Ó gbógun ti àwọn ará Filistia, ó sì wó odi Gati, ati ti Jabine ati ti Aṣidodu lulẹ̀. Ó kọ́ àwọn ìlú olódi ní agbègbè Aṣidodu ati ní ibòmíràn ní ilẹ̀ àwọn ará Filistia.

7. Ọlọrun ràn án lọ́wọ́, ó ṣẹgun àwọn ará Filistia ati àwọn ará Arabia tí wọ́n ń gbé Guribaali ati àwọn ará Meuni.

Ka pipe ipin Kronika Keji 26