Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Keji 26:2-11 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Ó tún Eloti kọ́, ó gbà á pada fún Juda lẹ́yìn ikú Amasaya, baba rẹ̀.

3. Ọmọ ọdún mẹrindinlogun ni Usaya nígbà tí ó jọba, ó sì wà lórí oyè ní Jerusalẹmu fún ọdún mejilelaadọta. Jekolaya, ará Jerusalẹmu ni ìyá rẹ̀.

4. Ó ṣe nǹkan tí ó tọ́ níwájú OLUWA, bí Amasaya baba rẹ̀.

5. Ó sin Ọlọrun nígbà ayé Sakaraya, nítorí pé Sakaraya ń kọ́ ọ ní ìbẹ̀rù Ọlọrun. Ní gbogbo àkókò tí ó fi ń sin Ọlọrun, Ọlọrun bukun un.

6. Ó gbógun ti àwọn ará Filistia, ó sì wó odi Gati, ati ti Jabine ati ti Aṣidodu lulẹ̀. Ó kọ́ àwọn ìlú olódi ní agbègbè Aṣidodu ati ní ibòmíràn ní ilẹ̀ àwọn ará Filistia.

7. Ọlọrun ràn án lọ́wọ́, ó ṣẹgun àwọn ará Filistia ati àwọn ará Arabia tí wọ́n ń gbé Guribaali ati àwọn ará Meuni.

8. Àwọn ará Amoni ń san ìṣákọ́lẹ̀ fún Usaya, òkìkí rẹ̀ kàn káàkiri títí dé agbègbè ilẹ̀ Ijipti, nítorí pé ó di alágbára gan-an.

9. Usaya tún kọ́ àwọn ilé ìṣọ́ ní Jerusalẹmu níbi Ẹnubodè tí ó wà ní igun odi, ati sí ibi Ẹnubodè àfonífojì, ati níbi Ìṣẹ́po Odi. Ó sì mọ odi sí wọn.

10. Ó tún kọ́ àwọn ilé ìṣọ́ sinu aṣálẹ̀, ó gbẹ́ ọpọlọpọ kànga, nítorí pé ó ní ọpọlọpọ agbo ẹran ọ̀sìn ní àwọn ẹsẹ̀ òkè ati ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Ó ní àwọn òṣìṣẹ́ tí wọn ń dá oko fún un ati àwọn tí wọn ń ṣiṣẹ́ ninu àjàrà, lórí òkè ati lórí àwọn ilẹ̀ ọlọ́ràá, nítorí ó fẹ́ràn iṣẹ́ àgbẹ̀.

11. Usaya ní ọpọlọpọ ọmọ ogun, tí wọ́n tó ogun lọ, ó pín wọn ní ìsọ̀rí-ìsọ̀rí gẹ́gẹ́ bí ètò tí Jeieli akọ̀wé, ati Maaseaya, ọ̀gágun ṣe, lábẹ́ àkóso Hananaya, ọ̀kan ninu àwọn ọ̀gágun ọba.

Ka pipe ipin Kronika Keji 26