orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jona 2 BIBELI MIMỌ (BM)

Adura Jona

1. Jona gbadura sí OLUWA Ọlọrun rẹ̀ láti inú ẹja náà,

2. ó ní, “Ninu ìpọ́njú mi, mo ké pe OLUWA,ó sì dá mi lóhùn,mo ké pè é láti inú isà òkú, ó sì gbóhùn mi.

3. Nítorí pé, ó gbé mi jù sinu ibú, ní ààrin agbami òkun,omi òkun sì bò mí mọ́lẹ̀;ọwọ́ agbára rírú omi òkun rẹ̀ sì ń wọ́ kọjá lórí mi.

4. Nígbà náà ni mo sọ pé,‘A ti ta mí nù kúrò níwájú rẹ;báwo ni n óo ṣe tún rí tẹmpili mímọ́ rẹ?’

5. Omi bò mí mọ́lẹ̀,ibú omi yí mi ká,koríko inú omi sì wé mọ́ mi lórí.

6. Mo já sí ibi tí ó jìn jùlọ ninu òkun,àní ibi tí ẹnikẹ́ni kò lọ ní àlọ-bọ̀ rí.Ṣugbọn ìwọ, OLUWA Ọlọrun mi,o mú ẹ̀mí mi jáde láti inú ibú náà.

7. Nígbà tí ẹ̀mí mi ń bọ́ lọ,mo gbadura sí ìwọ OLUWA,o sì gbọ́ adura mi ninu tẹmpili mímọ́ rẹ.

8. Àwọn tí wọn ń sin àwọn oriṣa lásánlàsàn kọ̀,wọn kò pa ìlérí wọn sí ọ mọ́.

9. Ṣugbọn n óo rúbọ sí ọ pẹlu ohùn ọpẹ́,n óo sì san ẹ̀jẹ́ mi.Ti OLUWA ni ìgbàlà!”

10. OLUWA bá pàṣẹ fún ẹja tí ó gbé Jona mì, ó sì lọ pọ̀ ọ́ sí èbúté, lórí ilẹ̀ gbígbẹ.