Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Joẹli 3:7-10 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Ṣugbọn nisinsinyii, n óo gbé wọn dìde níbi tí ẹ tà wọ́n sí, n óo sì gbẹ̀san ìwà yín lára ẹ̀yin alára.

8. N óo ta àwọn ọmọ yín ọkunrin ati àwọn ọmọ yín obinrin lẹ́rú fún àwọn ará Juda. Wọn yóo sì tà wọ́n fún àwọn ará Sabea, orílẹ̀-èdè tí ó jìnnà réré; nítorí OLUWA ni ó sọ bẹ́ẹ̀.”

9. Ẹ kéde èyí láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè.Ẹ múra ogun,ẹ rú àwọn akọni sókè.Kí gbogbo àwọn ọmọ ogun súnmọ́ tòsí,ogun yá!

10. Ẹ fi irin ọkọ́ yín rọ idà,ẹ fi dòjé yín rọ ọ̀kọ̀,kí àwọn tí wọn kò lágbára wí pé, “Ọmọ ogun ni mí.”

Ka pipe ipin Joẹli 3