Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 6:6-18 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Ǹjẹ́ ohun tí kò dùn ṣe é jẹláì fi iyọ̀ sí i?Tabi, adùn wo ní ń bẹ ninu funfun ẹyin?

7. Irú oúnjẹ bẹ́ẹ̀ kì í wù mí í jẹ,Ìríra ni jíjẹ rẹ̀ jẹ́ fún mi.

8. “Ìbá ti dára tó, kí Ọlọrun mú ìbéèrè mi ṣẹ,kí ó fún mi ní ohun tí ọkàn mi ń fẹ́.

9. Àní, kí ó wó mi mọ́lẹ̀,kí ó mú mi, kí ó pa mí dànù.

10. Yóo jẹ́ ìtùnú fún mi;n óo sì láyọ̀ ninu ọpọlọpọ ìrora,nítorí pé n kò sẹ́ ọ̀rọ̀ Ẹni Mímọ́.

11. Agbára wo ni mo ní,tí mo fi lè tún máa wà láàyè?Kí sì ni ìrètí mi, tí n óo fi tún máa ní sùúrù?

12. Agbára mi ha rí bí ti òkúta bí?Àbí ẹran ara mi jẹ́ idẹ?

13. Nítòótọ́, n kò ní agbára mọ́,bẹ́ẹ̀ ni n kò sì ní olùrànlọ́wọ́.

14. “Ẹni tí ó bá kọ̀tí kò ṣàánú ọ̀rẹ́ rẹ̀kò ní ìbẹ̀rù Olodumare.

15. Ṣugbọn, ẹ̀yin arakunrin mi,ẹlẹ́tàn ni yín, bíi odò àgbàrátí ó yára kún,tí ó sì tún yára gbẹ,

16. tí yìnyín bo odò náà tóbẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣókùnkùn,tí yìnyín ńláńlá sì farapamọ́ sibẹ,

17. ṣugbọn ní àkókò ooru, wọn a yọ́,bí ilẹ̀ bá ti gbóná,wọn a sì gbẹ.

18. Àwọn oníṣòwò tí ń lo ràkúnmíyà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n ń wá omi kiriwọ́n kiri títí wọ́n fi ṣègbé ninu aṣálẹ̀.

Ka pipe ipin Jobu 6