Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 6:13-30 BIBELI MIMỌ (BM)

13. Nítòótọ́, n kò ní agbára mọ́,bẹ́ẹ̀ ni n kò sì ní olùrànlọ́wọ́.

14. “Ẹni tí ó bá kọ̀tí kò ṣàánú ọ̀rẹ́ rẹ̀kò ní ìbẹ̀rù Olodumare.

15. Ṣugbọn, ẹ̀yin arakunrin mi,ẹlẹ́tàn ni yín, bíi odò àgbàrátí ó yára kún,tí ó sì tún yára gbẹ,

16. tí yìnyín bo odò náà tóbẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣókùnkùn,tí yìnyín ńláńlá sì farapamọ́ sibẹ,

17. ṣugbọn ní àkókò ooru, wọn a yọ́,bí ilẹ̀ bá ti gbóná,wọn a sì gbẹ.

18. Àwọn oníṣòwò tí ń lo ràkúnmíyà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n ń wá omi kiriwọ́n kiri títí wọ́n fi ṣègbé ninu aṣálẹ̀.

19. Àwọn oníṣòwò Temani ń wò rá rà rá,àwọn ọ̀wọ́ èrò Ṣeba sì dúró pẹlu ìrètí.

20. Ìrètí wọn di òfonítorí wọ́n ní ìdánilójú.Wọ́n dé ibi tí odò wà tẹ́lẹ̀,ṣugbọn òfo ni wọ́n bá.

21. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ rí sí mi nisinsinyii.Ẹ rí ìdààmú mi, ẹ̀rù bà yín.

22. Ǹjẹ́ mo tọrọ ẹ̀bùn lọ́wọ́ yín?Tabi mo bẹ̀ yín pé kí ẹ mú ninu owó yín,kí ẹ fi san àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí mi?

23. Ǹjẹ́ mo bẹ̀ yín pé kí ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá;tabi pé kí ẹ rà mí pada kúrò lọ́wọ́ aninilára?

24. “Ó dára, mo gbọ́, ẹ wá kọ́ mi,ẹ ṣàlàyé ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ṣẹ̀ fún mi;n óo sì dákẹ́ n óo tẹ́tí sílẹ̀.

25. Lóòótọ́ ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní agbára,ṣugbọn kí ni ẹ̀ ń bá mi wí lé lórí.

26. Ẹ rò pé mò ń fi ọ̀rọ̀ ṣòfò lásán ni?Kí ni ẹ̀ ń dásí ọ̀rọ̀ èmi onírora sí?

27. Ẹ tilẹ̀ lè ṣẹ́ gègé lórí ọmọ òrukàn,ẹ sì lè díye lé ọ̀rẹ́ yín.

28. “Ẹ gbọ́, ẹ wò mí dáradára,nítorí n kò ní purọ́ níwájú yín.

29. Mo bẹ̀ yín, ẹ dúró bẹ́ẹ̀,kí ẹ má baà ṣẹ̀.Ẹ dúró bẹ́ẹ̀, nítorí n kò lẹ́bi.

30. Ṣé ẹ rò pé mò ń parọ́ ni?Àbí n kò mọ nǹkan burúkú yàtọ̀?

Ka pipe ipin Jobu 6