Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 41:14-32 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Ta ló tó ya ẹnu rẹ̀?Gbogbo eyín rẹ̀ ni ó kún fún ẹ̀rù.

15. Ẹ̀yìn rẹ̀ kún fún ìpẹ́ tí ó dàbí apata,a tò wọ́n lẹ́sẹẹsẹ, wọ́n súnmọ́ ara wọn pẹ́kípẹ́kí bí èdìdì.

16. Àwọn ìpẹ́ náà lẹ̀ mọ́ ara wọn tímọ́tímọ́,tóbẹ́ẹ̀ tí afẹ́fẹ́ kò lè fẹ́ kọjá láàrin wọn.

17. Wọ́n so pọ̀,wọ́n lẹ̀ mọ́ ara wọn tóbẹ́ẹ̀,tí ohunkohun kò lè ṣí wọn.

18. Bí ó bá sín, ìmọ́lẹ̀ á tàn jáde ní imú rẹ̀,ojú rẹ̀ ń tàn bíi ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ kutukutu.

19. Ahọ́n iná ń yọ lẹ́nu rẹ̀ bí iná tí ń ta jáde,bẹ́ẹ̀ ni ahọ́n iná ń yọ lálá.

20. Èéfín ń jáde ní imú rẹ̀,bíi ti ìkòkò gbígbóná ati ìgbẹ́ tí ń jó.

21. Èémí tí ó ń mí jáde dàbí ògúnná,ahọ́n iná ń yọ ní ẹnu rẹ̀.

22. Kìkì agbára ni ọrùn rẹ̀,ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ sì ń bẹ níwájú rẹ̀.

23. Ìṣẹ́po ẹran ara rẹ̀ lẹ̀ pọ̀ mọ́ ara wọn,wọ́n lẹ̀ pọ̀, wọn kò sì ṣe é ṣí.

24. Ọkàn rẹ̀ le bí òkúta,ó le ju ọlọ lọ.

25. Bí ó bá dìde, ẹ̀rù á ba àwọn alágbára,wọn á bì sẹ́yìn, wọn á ṣubú lé ara wọn lórí.

26. Bí idà tilẹ̀ bá a, kò ràn án,bẹ́ẹ̀ náà ni ọ̀kọ̀, ati ọfà, ati ẹ̀sín.

27. Irin kò yàtọ̀ sí koríko lójú rẹ̀,idẹ sì dàbí igi tí ó ti rà.

28. Bí wọn ta á lọ́fà, kò ní torí rẹ̀ sá,àwọn òkúta kànnàkànnà dàbí àgékù koríko lójú rẹ̀.

29. Kùmọ̀ dàbí koríko lára rẹ̀,a sì máa fi ẹni tí ó ju ọ̀kọ̀ lù ú rẹ́rìn-ín.

30. Ìpẹ́ ikùn rẹ̀ dàbí àpáàdì tí ó mú,wọn ń fa ilẹ̀ tútù ya bí ọkọ́.

31. Ó mú kí ibú hó bí omi inú ìkòkò,ó ṣe òkun bí ìkòkò òróró ìpara.

32. Bí ó bá ń rìn lọ, ipa ọ̀nà rẹ̀ a máa hàn lẹ́yìn rẹ̀,eniyan á rò pé òkun ń hó bí ọṣẹ ni.

Ka pipe ipin Jobu 41