Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 40:8-18 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ṣé o fẹ́ sọ pé mò ń ṣe àìdára ni?O fẹ́ dá mi lẹ́bi kí á lè dá ọ láre?

9. Ṣé o lágbára bí èmi Ọlọrun,àbí o lè sán wàá bí ààrá, nígbà tí o bá ń sọ̀rọ̀?

10. Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, fi ọlá ati ìyìn ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́,kí o sì fi ògo ati ẹwà bo ara rẹ bí aṣọ.

11. Fi ibinu rẹ hàn, wo gbogbo àwọn agbéraga,kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.

12. Wo gbogbo àwọn agbéraga, kí o sì sọ wọ́n di yẹpẹrẹ,rún àwọn ẹni ibi mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.

13. Bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ papọ̀,dì wọ́n ní ìgbèkùn sí ipò òkú.

14. Nígbà náà ni n óo gbà pé,agbára rẹ lè fún ọ ní ìṣẹ́gun.

15. “Wo Behemoti, ẹran ńlá inú omi,tí mo dá gẹ́gẹ́ bí mo ti dá ọ,koríko ni ó ń jẹ bíi mààlúù!

16. Wò ó bí ó ti lágbára tó!Ati irú okun tí awọ inú rẹ̀ ní.

17. Ìrù rẹ̀ dúró ṣánṣán bí igi kedari,gbogbo iṣan itan rẹ̀ dì pọ̀.

18. Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá idẹ,ọwọ́ ati ẹsẹ̀ rẹ̀ rí bí irin.

Ka pipe ipin Jobu 40