Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 40:2-9 BIBELI MIMỌ (BM)

2. “Ṣé ẹni tí ń bá eniyan rojọ́ lè bá Olodumare rojọ́?Kí ẹni tí ń bá Ọlọrun jiyàn dáhùn.”

3. Nígbà náà ni Jobu dá OLUWA lóhùn, ó ní:

4. “OLUWA, kí ni mo jámọ́,tí n óo fi dá ọ lóhùn?Nítorí náà, mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.

5. Mo ti sọ̀rọ̀ ju bí ó ti yẹ lọ,n kò sì ní sọ̀rọ̀ mọ́.”

6. Nígbà náà ni OLUWA tún bá Jobu sọ̀rọ̀ láti inú ìjì líle, ó ní,

7. “Múra gírí bí ọkunrin,mo ní ìbéèrè láti bi ọ́, o óo sì dá mi lóhùn.

8. Ṣé o fẹ́ sọ pé mò ń ṣe àìdára ni?O fẹ́ dá mi lẹ́bi kí á lè dá ọ láre?

9. Ṣé o lágbára bí èmi Ọlọrun,àbí o lè sán wàá bí ààrá, nígbà tí o bá ń sọ̀rọ̀?

Ka pipe ipin Jobu 40