Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 39:1-19 BIBELI MIMỌ (BM)

1. “Ǹjẹ́ o mọ ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ?Ṣé o ti ká àgbọ̀nrín mọ́ ibi tí ó ti ń bímọ rí?

2. Ǹjẹ́ o lè ka iye oṣù tí wọ́n fi ń lóyún?Tabi o mọ ìgbà tí wọ́n bímọ?

3. Ǹjẹ́ o mọ ìgbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀,tí wọ́n sì bímọ?

4. Àwọn ọmọ wọn á di alágbára,wọn á dàgbà ninu pápá,wọn á sì lọ, láìpadà wá sọ́dọ̀ àwọn òbí wọn mọ́.

5. “Ta ló fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ lómìniratí ó sì tú ìdè rẹ̀?

6. Mo fi inú pápá ṣe ilé rẹ̀,ilẹ̀ oníyọ̀ sì di ibùgbé rẹ̀.

7. Ó ń pẹ̀gàn ìdàrúdàpọ̀ inú ìlú ńlá,kò gbọ́ ariwo àwọn tí wọn ń fi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ṣiṣẹ́.

8. Ó ń rìn káàkiri àwọn òkè bí ibùjẹ rẹ̀,ó sì ń wá ewéko tútù kiri.

9. “Ṣé ẹfọ̀n ṣetán láti sìn ọ́?Ṣé yóo wá sùn ní ibùjẹ ẹran rẹ lálẹ́?

10. Ṣé o lè so àjàgà mọ́ ọn lọ́rùn ní poro oko,tabi kí ó máa kọ ebè tẹ̀lé ọ?

11. Ṣé o lè gbẹ́kẹ̀lé e nítorí pé agbára rẹ̀ pọ̀,tabi kí o fi iṣẹ́ rẹ sílẹ̀ fún un láti ṣe?

12. Ṣé o ní igbagbọ pé yóo pada,ati pé yóo ru ọkà rẹ̀ wá sí ibi ìpakà rẹ?

13. “Ògòǹgò lu ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ninu ọláńlá rẹ̀,ṣugbọn kò lè fò bí ẹyẹ àkọ̀?

14. Ó yé ẹyin rẹ̀ sórí ilẹ̀,kí ooru ilẹ̀ lè mú wọn,

15. ó gbàgbé pé ẹnìkan le tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ kí wọn sì fọ́,ati pé ẹranko ìgbẹ́ lè fọ́ wọn.

16. Ògòǹgò kò náání àwọn ọmọ rẹ̀,ó ń ṣe sí wọn bí ẹni pé kì í ṣe òun ló bí wọn,kò bìkítà bí wahala rẹ̀ tilẹ̀ já sí asán;

17. nítorí pé Ọlọrun kò fún un ní ọgbọ́n ati òye.

18. Ṣugbọn nígbà tí ó bá ṣetán ati sáré,a máa fi ẹṣin ati ẹni tí ó gùn ún ṣe yẹ̀yẹ́.

19. “Ṣé ìwọ ni o fún ẹṣin lágbára,tí o sì fi agbára ṣe gọ̀gọ̀ sí i lọ́rùn?

Ka pipe ipin Jobu 39