Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 37:8-23 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Àwọn ẹranko wọ ihò wọn lọ,wọ́n dákẹ́ sibẹ, wọ́n sá pamọ́.

9. Ìjì líle fẹ́ jáde láti inú yàrá rẹ̀,òtútù sì mú wá láti inú afẹ́fẹ́ tí ń fẹ́.

10. Yìnyín ti inú èémí Ọlọrun wá,gbogbo omi inú odò sì dì.

11. Ó fi omi kún inú ìkùukùu,ìkùukùu sì fọ́n mànàmáná rẹ̀ ká.

12. Wọ́n ń yípo lábẹ́ ìtọ́ni rẹ̀,láti mú gbogbo àṣẹ tí ó pa ṣẹ, lórí ilẹ̀ alààyè.

13. Ó mú kí àwọn nǹkan wọnyi ṣẹlẹ̀,bóyá fún àtúnṣe ni, tabi nítorí ilẹ̀ rẹ̀,tabi láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.

14. “Fetí sílẹ̀, ìwọ Jobu,dúró kí o sì ronú nípa àwọn iṣẹ́ ìyanu Ọlọrun.

15. Ǹjẹ́ o mọ bí Ọlọrun ṣe pàṣẹ,tí ó sì mú kí mànàmáná awọsanma tàn?

16. Ǹjẹ́ o mọ̀ bí ó ṣe so awọsanma rọ̀,iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ ni;

17. ìwọ tí ooru mú nígbà tí ayé dákẹ́ rọ́rọ́nítorí pé afẹ́fẹ́ ìhà gúsù kò fẹ́?

18. Ṣé o lè tẹ́ ojú ọ̀run bí ó ti tẹ́ ẹ,kí ó le, kí ó sì dàbí dígí tí ń dán?

19. Kọ́ wa ní ohun tí a lè bá Ọlọrun sọ,a kò lè kó àròyé wa jọ siwaju rẹ̀,nítorí àìmọ̀kan wa.

20. Ṣé kí n sọ fún Ọlọrun pé n ó bá a sọ̀rọ̀ ni?Ta ni yóo fẹ́ kí á gbé òun mì?

21. “Ẹnikẹ́ni kò lè wo ìmọ́lẹ̀ ojú ọ̀runnígbà tí ó bá ń tàn ní awọsanma,nígbà tí afẹ́fẹ́ bá fẹ́ tí ó sì gbá wọn lọ.

22. Láti ìhà àríwá ni Ọlọrun ti yọ,ó fi ọlá ńlá, tí ó bani lẹ́rù, bora bí aṣọ.

23. Àwámárìídìí ni Olodumare–agbára ati ìdájọ́ òtítọ́ rẹ̀ pọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kì í kọ òdodo sílẹ̀.

Ka pipe ipin Jobu 37