18. Ṣé o lè tẹ́ ojú ọ̀run bí ó ti tẹ́ ẹ,kí ó le, kí ó sì dàbí dígí tí ń dán?
19. Kọ́ wa ní ohun tí a lè bá Ọlọrun sọ,a kò lè kó àròyé wa jọ siwaju rẹ̀,nítorí àìmọ̀kan wa.
20. Ṣé kí n sọ fún Ọlọrun pé n ó bá a sọ̀rọ̀ ni?Ta ni yóo fẹ́ kí á gbé òun mì?
21. “Ẹnikẹ́ni kò lè wo ìmọ́lẹ̀ ojú ọ̀runnígbà tí ó bá ń tàn ní awọsanma,nígbà tí afẹ́fẹ́ bá fẹ́ tí ó sì gbá wọn lọ.
22. Láti ìhà àríwá ni Ọlọrun ti yọ,ó fi ọlá ńlá, tí ó bani lẹ́rù, bora bí aṣọ.
23. Àwámárìídìí ni Olodumare–agbára ati ìdájọ́ òtítọ́ rẹ̀ pọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kì í kọ òdodo sílẹ̀.
24. Nítorí náà, gbogbo eniyan bẹ̀rù rẹ̀,kò sì náání àwọn tí wọ́n gbọ́n lójú ara wọn.”