Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 36:17-33 BIBELI MIMỌ (BM)

17. “Ṣugbọn, ìdájọ́ eniyan burúkú dé bá ọ,ọwọ́ ìdájọ́ ati òdodo sì ti tẹ̀ ọ́.

18. Ṣọ́ra kí ibinu má baà sọ ọ́ di ẹlẹ́yà,kí títóbi àbẹ̀tẹ́lẹ̀ sì mú ọ ṣìnà.

19. Igbe ati agbára rẹ kò lè gbà ọ́ kúrò ninu ìpọ́njú.

20. Má máa dúró, kí o máa retí ọjọ́ alẹ́,nígbà tí à ń pa àwọn eniyan run.

21. Ṣọ́ra kí o má yipada sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀,tí ó wù ọ́ ju ìjìyà lọ.

22. “Wò ó, a gbé OLUWA ga ninu agbára rẹ̀;ta ni olùkọ́ tí ó dàbí rẹ̀?

23. Ta ló ń sọ ohun tí yóo ṣe fún un,tabi kí ó sọ fún un pé, ‘Ohun tí o ṣe yìí kò dára?’

24. Ranti láti gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,tí àwọn eniyan ń kọrin nípa rẹ̀.

25. Gbogbo eniyan ti rí i;àwọn tí wọ́n wà ní òkèèrè ń wò ó.

26. Wò ó, Ọlọrun tóbi lọ́ba, ju ìmọ̀ wa lọ,kò sí ẹni tí ó lè mọ ọjọ́ orí rẹ̀.

27. “Ó fa ìkán omi sókè láti inú ilẹ̀,ó sọ ìkùukùu di òjò,

28. ó sì rọ òjò sílẹ̀ láti ojú ọ̀runsórí ọmọ eniyan lọpọlọpọ.

29. Ta ló mọ bí ó ti tẹ́ ìkùukùu?Tabi bí ó ṣe ń sán ààrá láti inú àgọ́ rẹ̀?

30. Ó fi mànàmáná yí ara rẹ̀ ká,ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.

31. Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe ń ṣàkóso àwọn orílẹ̀-èdè;ó sì ń fún wọn ní oúnjẹ lọpọlọpọ.

32. Ìkáwọ́ rẹ̀ ni mànàmáná wà,ó sì ń rán ààrá láti sán lu ohun tí ó bá fẹ́.

33. Ìró ààrá ń kéde bíbọ̀ rẹ̀,àwọn ẹran ọ̀sìn sì mọ̀ pé ó súnmọ́ tòsí.

Ka pipe ipin Jobu 36