27. Yóo wá sọ gbangba níwájú àwọn eniyan pé,‘Mo ti ṣẹ̀, mo sì ti yí ẹ̀tọ́ po,ṣugbọn Ọlọrun kò jẹ mí níyà ẹ̀ṣẹ̀ mi.
28. Ó ti ra ọkàn mi pada kúrò lọ́wọ́ isà òkú,mo sì wà láàyè.’
29. “Wò ó, Ọlọrun a máa ṣe nǹkan wọnyi léraléra fún eniyan,lẹẹmeji tabi lẹẹmẹta,
30. láti lè gba ọkàn rẹ̀ là lọ́wọ́ ikú,kí ó lè wà láàyè.
31. “Gbọ́, ìwọ Jobu, farabalẹ̀,dákẹ́ kí o lè gbọ́ ohun tí n óo sọ.
32. Bí o bá ní ohunkohun láti sọ, dá mi lóhùn;sọ̀rọ̀, nítorí pé mo fẹ́ dá ọ láre ni.
33. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, tẹ́tí sí mi;farabalẹ̀, n óo sì kọ́ ọ lọ́gbọ́n.”