Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 31:28-35 BIBELI MIMỌ (BM)

28. Èyí pẹlu yóo jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,tí adájọ́ gbọdọ̀ jẹ mí níyà fún;nítorí yóo jẹ́ aiṣootọ sí Ọlọrun ọ̀run.

29. “Bí mo bá yọ̀ nítorí ìparun ẹni tí ó kórìíra mi,tabi kí inú mi dùn nígbà tí ohun burúkú bá ṣẹlẹ̀ sí i.

30. (N kò fi ẹnu mi ṣẹ̀kí n gbé e ṣépè pé kí ó lè kú);

31. bí àwọn tí wọn ń gbé inú àgọ́ mi kò bá wí pé,‘Ta ló kù tí kò tíì yó?’

32. (Kò sí àlejò tí ń sun ìta gbangba,nítorí ìlẹ̀kùn ilé mi ṣí sílẹ̀ fún àwọn arìnrìnàjò);

33. bí mo bá fi ẹ̀ṣẹ̀ mi pamọ́ fún eniyan,tí mo sì dé àìdára mi mọ́ra,

34. nítorí pé mò ń bẹ̀rù ọpọlọpọ eniyan,ẹ̀gàn ìdílé sì ń dẹ́rùbà mí,tóbẹ́ẹ̀ tí mo fi dákẹ́, tí n kò sì jáde síta.

35. Ha! Ǹ bá rí ẹni gbọ́ tèmi!(Mo ti tọwọ́ bọ̀wé,kí Olodumare dá mi lóhùn!)Ǹ bá lè ní àkọsílẹ̀ ẹ̀sùn tí àwọn ọ̀tá fi kàn mí!

Ka pipe ipin Jobu 31