Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 31:26-33 BIBELI MIMỌ (BM)

26. Tí mo bá ti wo oòrùn nígbà tí ó ń ràn,tabi tí mo wo òṣùpá ninu ẹwà rẹ̀:

27. tí ọkàn mi fà sí wọn;tí mo sì tẹ́wọ́ adura sí wọn.

28. Èyí pẹlu yóo jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,tí adájọ́ gbọdọ̀ jẹ mí níyà fún;nítorí yóo jẹ́ aiṣootọ sí Ọlọrun ọ̀run.

29. “Bí mo bá yọ̀ nítorí ìparun ẹni tí ó kórìíra mi,tabi kí inú mi dùn nígbà tí ohun burúkú bá ṣẹlẹ̀ sí i.

30. (N kò fi ẹnu mi ṣẹ̀kí n gbé e ṣépè pé kí ó lè kú);

31. bí àwọn tí wọn ń gbé inú àgọ́ mi kò bá wí pé,‘Ta ló kù tí kò tíì yó?’

32. (Kò sí àlejò tí ń sun ìta gbangba,nítorí ìlẹ̀kùn ilé mi ṣí sílẹ̀ fún àwọn arìnrìnàjò);

33. bí mo bá fi ẹ̀ṣẹ̀ mi pamọ́ fún eniyan,tí mo sì dé àìdára mi mọ́ra,

Ka pipe ipin Jobu 31