Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 31:13-21 BIBELI MIMỌ (BM)

13. “Bí mo bá kọ̀ láti fetí sí ẹjọ́ àwọniranṣẹkunrin ati iranṣẹbinrin mi,nígbà tí wọ́n bá fẹ̀sùn kàn mí,

14. báwo ni n óo ṣe dúró níwájú Ọlọrun?Kí ni kí n wí nígbà tí ó bá bèèrè lọ́wọ́ mi?

15. Ṣebí ẹni tí ó dá mi ninu oyún,òun kan náà ló dá iranṣẹ mi?Òun ló mọ wá kí wọn tó bí wa.

16. “Bí mo bá fi ohunkohun pọ́n talaka lójú rí,tabi kí n fi opó sílẹ̀ ninu àìní,

17. tabi kí n dá oúnjẹ mi jẹ,láìfún ọmọ aláìníbaba jẹ

18. (láti ìgbà èwe rẹ̀ ni mo ti ń ṣe bíi baba fún un,tí mo sì ń tọ́jú rẹ̀ láti inú ìyá rẹ̀);

19. bí mo bá ti rí ẹni tí ó ń kú lọ,nítorí àìrí aṣọ bora,tabi talaka tí kò rí ẹ̀wù wọ̀,

20. kí ó sì súre fún mi,nítorí pé ara rẹ̀ móorupẹlu aṣọ tí a fi irun aguntan mi hun,

21. bí mo bá fi ìyà jẹ aláìníbaba,nítorí pé mo mọ eniyan ní ilé ẹjọ́,

Ka pipe ipin Jobu 31