Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 30:16-25 BIBELI MIMỌ (BM)

16. “Nisinsinyii, ẹ̀mí mi fò lọ ninu mi,ọjọ́ ìjìyà sì dé bá mi.

17. Ní òru, egungun ń ro mí,ìrora mi kò sì dínkù.

18. Ọlọrun fi ipá gba aṣọ mi,ó fún mi lọ́rùn bí ọrùn ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ mi.

19. Ó sọ mí sinu ẹrẹ̀,mo dàbí eruku ati eérú.

20. “Mo ké pè ọ́, Ọlọrun, O kò dáhùn,mo dìde dúró, mo gbadura, o kò kà mí sí.

21. O dojú ibinu kọ mí,o fi agbára rẹ bá mi jà.

22. O sọ mí sókè ninu afẹ́fẹ́,ò ń bì mí síhìn-ín sọ́hùn-únláàrin ariwo ìjì líle.

23. Dájúdájú mo mọ̀ pé o óo gbé mi lọ sí ipò òkú,ilé tí o yàn fún gbogbo eniyan.

24. Bí ẹni tí a ti là mọ́lẹ̀, tí kò lè dìde, bá ń kígbe fún ìrànlọ́wọ́ ninu ìnira,dájúdájú o kò tún ní gbé ìjà kò ó?

25. Ṣebí mo ti sọkún nítorí àwọn tí wọ́n wà ninu ìṣòro rí,tí mo sì káàánú àwọn aláìní.

Ka pipe ipin Jobu 30