15. Ìbẹ̀rù-bojo dé bá mi,wọ́n ń lépa ọlá mi bí afẹ́fẹ́,ọlà mi sì parẹ́ bí ìkùukùu.
16. “Nisinsinyii, ẹ̀mí mi fò lọ ninu mi,ọjọ́ ìjìyà sì dé bá mi.
17. Ní òru, egungun ń ro mí,ìrora mi kò sì dínkù.
18. Ọlọrun fi ipá gba aṣọ mi,ó fún mi lọ́rùn bí ọrùn ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ mi.
19. Ó sọ mí sinu ẹrẹ̀,mo dàbí eruku ati eérú.
20. “Mo ké pè ọ́, Ọlọrun, O kò dáhùn,mo dìde dúró, mo gbadura, o kò kà mí sí.
21. O dojú ibinu kọ mí,o fi agbára rẹ bá mi jà.
22. O sọ mí sókè ninu afẹ́fẹ́,ò ń bì mí síhìn-ín sọ́hùn-únláàrin ariwo ìjì líle.
23. Dájúdájú mo mọ̀ pé o óo gbé mi lọ sí ipò òkú,ilé tí o yàn fún gbogbo eniyan.
24. Bí ẹni tí a ti là mọ́lẹ̀, tí kò lè dìde, bá ń kígbe fún ìrànlọ́wọ́ ninu ìnira,dájúdájú o kò tún ní gbé ìjà kò ó?
25. Ṣebí mo ti sọkún nítorí àwọn tí wọ́n wà ninu ìṣòro rí,tí mo sì káàánú àwọn aláìní.
26. Ṣugbọn nígbà tí mo bá ń retí ohun rere,ibi ní ń bá mi.Nígbà tí mo bá sì ń retí ìmọ́lẹ̀,òkùnkùn ni mò ń rí.
27. Ọkàn mi dàrú, ara mi kò balẹ̀,ọjọ́ ìpọ́njú dé bá mi.
28. Mo fa ojú ro, mò ń káàkiri,mo dìde nàró láti bèèrè ìrànlọ́wọ́ láàrin àwùjọ.
29. Mò ń kígbe arò bí ajáko,mo di ẹgbẹ́ ẹyẹ ògòǹgò.
30. Àwọ̀ ara mi di dúdú, ó ń bó,egungun mi gbóná fún ooru.
31. Ọ̀fọ̀ dípò orin ayọ̀ fún mi,ẹkún sì dípò ohùn fèrè.