13. Wọ́n dínà mọ́ mi,wọ́n dá kún wahala mi,kò sì sí ẹni tí ó lè dá wọn lẹ́kun.
14. Wọ́n jálù mí, bí ìgbà tí ọpọlọpọ ọmọ ogun bá gba ihò ara odi ìlú wọlé,wọ́n ya lù mí, wọ́n wó mi mọ́lẹ̀.
15. Ìbẹ̀rù-bojo dé bá mi,wọ́n ń lépa ọlá mi bí afẹ́fẹ́,ọlà mi sì parẹ́ bí ìkùukùu.
16. “Nisinsinyii, ẹ̀mí mi fò lọ ninu mi,ọjọ́ ìjìyà sì dé bá mi.
17. Ní òru, egungun ń ro mí,ìrora mi kò sì dínkù.
18. Ọlọrun fi ipá gba aṣọ mi,ó fún mi lọ́rùn bí ọrùn ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ mi.
19. Ó sọ mí sinu ẹrẹ̀,mo dàbí eruku ati eérú.
20. “Mo ké pè ọ́, Ọlọrun, O kò dáhùn,mo dìde dúró, mo gbadura, o kò kà mí sí.
21. O dojú ibinu kọ mí,o fi agbára rẹ bá mi jà.
22. O sọ mí sókè ninu afẹ́fẹ́,ò ń bì mí síhìn-ín sọ́hùn-únláàrin ariwo ìjì líle.
23. Dájúdájú mo mọ̀ pé o óo gbé mi lọ sí ipò òkú,ilé tí o yàn fún gbogbo eniyan.
24. Bí ẹni tí a ti là mọ́lẹ̀, tí kò lè dìde, bá ń kígbe fún ìrànlọ́wọ́ ninu ìnira,dájúdájú o kò tún ní gbé ìjà kò ó?
25. Ṣebí mo ti sọkún nítorí àwọn tí wọ́n wà ninu ìṣòro rí,tí mo sì káàánú àwọn aláìní.
26. Ṣugbọn nígbà tí mo bá ń retí ohun rere,ibi ní ń bá mi.Nígbà tí mo bá sì ń retí ìmọ́lẹ̀,òkùnkùn ni mò ń rí.