Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 3:15-26 BIBELI MIMỌ (BM)

15. tabi pẹlu àwọn ọmọ aládé tí wọ́n ní wúrà,tí fadaka sì kún ilé wọn.

16. Tabi kí n rí bí ọmọtí a bí ní ọjọ́ àìpé,tí a bò mọ́lẹ̀ láì tíì lajú sáyé.

17. Níbi tí àwọn oníṣẹ́ ibi kò ti lágbára mọ́,tí àwọn tí gbogbo nǹkan ti sú gbé ń sinmi.

18. Níbẹ̀, àwọn ẹlẹ́wọ̀n ń gbé pọ̀ pẹlu ìrọ̀rùn,wọn kò sì gbọ́ ohùn akóniṣiṣẹ́ mọ́.

19. Àwọn mẹ̀kúnnù ati àwọn eniyan pataki pataki jọ wà níbẹ̀,àwọn ẹrú sì bọ́ lọ́wọ́ oluwa wọn.

20. “Kí ló dé tí a fi ìmọ́lẹ̀fún ẹni tí ń kérora,tí a fi ẹ̀mí fún ẹni tí inú rẹ̀ bàjẹ́;

21. tí ó ń wá ikú,ṣugbọn tí kò rí;tí ó ń wá ikú lójú mejeejiju ẹni tí ń wá ìṣúra tí a fi pamọ́ lọ?

22. Àwọn tí inú wọn ìbá dùn lọpọlọpọbí wọ́n bá rí ẹni gbé wọn sin.

23. Kí ló dé tí a fi fi ìmọ́lẹ̀fún ẹni tí ọ̀nà dàrú mọ́ lójú;ẹni tí Ọlọrun ti tì sinu àhámọ́?

24. Nítorí ìmí ẹ̀dùn di oúnjẹ fún mi,ìráhùn mi sì ń tú jáde bí omi.

25. Ohun tí mo bẹ̀rù jù ti dé bá mi,ohun tí ń fò mí láyà ti ṣẹlẹ̀ sí mi.

26. N kò ní alaafia,bẹ́ẹ̀ ni ara kò rọ̀ mí,n kò sì ní ìsinmi, àfi ìyọnu.”

Ka pipe ipin Jobu 3