Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 3:11-21 BIBELI MIMỌ (BM)

11. “Kí ló dé tí n kò kúnígbà tí ìyá mi ń rọbí lọ́wọ́, tí ó fẹ́ bí mi,tabi kí n kú, lẹsẹkẹsẹ tí wọ́n bí mi?

12. Kí ló dé tí ìyá mi gbé mi lẹ́sẹ̀?Kí ló dé tí ó fi fún mi lọ́mú?

13. Ǹ bá ti dùbúlẹ̀,ǹ bá ti dákẹ́ jẹ́ẹ́;ǹ bá ti sùn,ǹ bá sì ti máa sinmi

14. pẹlu àwọn ọba ati àwọn ìgbìmọ̀ àgbáyé, tí wọ́n ti sùn,àwọn tí wọ́n tún àlàpà kọ́ fún ara wọn;

15. tabi pẹlu àwọn ọmọ aládé tí wọ́n ní wúrà,tí fadaka sì kún ilé wọn.

16. Tabi kí n rí bí ọmọtí a bí ní ọjọ́ àìpé,tí a bò mọ́lẹ̀ láì tíì lajú sáyé.

17. Níbi tí àwọn oníṣẹ́ ibi kò ti lágbára mọ́,tí àwọn tí gbogbo nǹkan ti sú gbé ń sinmi.

18. Níbẹ̀, àwọn ẹlẹ́wọ̀n ń gbé pọ̀ pẹlu ìrọ̀rùn,wọn kò sì gbọ́ ohùn akóniṣiṣẹ́ mọ́.

19. Àwọn mẹ̀kúnnù ati àwọn eniyan pataki pataki jọ wà níbẹ̀,àwọn ẹrú sì bọ́ lọ́wọ́ oluwa wọn.

20. “Kí ló dé tí a fi ìmọ́lẹ̀fún ẹni tí ń kérora,tí a fi ẹ̀mí fún ẹni tí inú rẹ̀ bàjẹ́;

21. tí ó ń wá ikú,ṣugbọn tí kò rí;tí ó ń wá ikú lójú mejeejiju ẹni tí ń wá ìṣúra tí a fi pamọ́ lọ?

Ka pipe ipin Jobu 3