Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 29:3-14 BIBELI MIMỌ (BM)

3. nígbà tí ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ń tàn sí mi lórí,tí mo kọjá ninu òkùnkùn pẹlu ìmọ́lẹ̀ rẹ̀;

4. kí ó tún rí fún mi bí ìgbà tí ara dẹ̀ mí,nígbà tí ìrẹ́pọ̀ wà láàrin Ọlọrun ati ìdílé mi;

5. tí Olodumare wà pẹlu mi,tí gbogbo àwọn ọmọ mi yí mi ká;

6. tí mò ń rí ọpọlọpọ wàrà lára àwọn ẹran ọ̀sìn mi,ati ọpọlọpọ òróró lára igi olifi tí ń dàgbà láàrin òkúta!

7. Nígbà tí mo lọ sí ẹnubodè ìlú,tí mo jókòó ní gbàgede,

8. tí àwọn ọdọmọkunrin bá rí mi, wọn á bìlà sẹ́gbẹ̀ẹ́ kan,àwọn àgbà á sì dìde dúró;

9. àwọn ìjòyè á dákẹ́ rọ́rọ́,wọn á fi ọwọ́ bo ẹnu wọn.

10. Àwọn olórí á panumọ́,ahọ́n wọn á lẹ̀ mọ́ wọn lẹ́nu.

11. Àwọn tí wọ́n gbọ́ nípa mi, ń pè mí ní ẹni ibukun,àwọn tí wọ́n rí mi ń kan sáárá sí mi.

12. Nítorí pé mò ń ran àwọn aláìní tí ń ké lọ́wọ́,ati àwọn aláìníbaba tí wọn kò ní olùrànlọ́wọ́.

13. Ìre àwọn tí ń kú lọ mọ́ mi,mo sì mú kí opó kọrin ayọ̀.

14. Mo fi òdodo bora bí aṣọ,ìdájọ́ òtítọ́ dàbí ẹ̀wù ati adé mi.

Ka pipe ipin Jobu 29