22. Ìparun ati ikú jẹ́wọ́ pé,‘Àhesọ ni ohun tí a gbọ́ nípa rẹ̀.’
23. “Ọlọrun nìkan ló mọ ọ̀nà rẹ̀,òun nìkan ló mọ ibùjókòó rẹ̀.
24. Nítorí pé ó ń wo gbogbo ayé,ó sì ń rí ohun gbogbo tí ó wà lábẹ́ ọ̀run.
25. Nígbà tí ó fún afẹ́fẹ́ ní agbára,tí ó sì ṣe ìdíwọ̀n omi,
26. nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò,tí ó sì lànà fún mànàmáná.
27. Lẹ́yìn náà ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde,ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, ó sì dán an wò.
28. Nígbà náà ni ó sọ fún eniyan pé,‘Wò ó, ìbẹ̀rù OLUWA ni ọgbọ́n,kí á yẹra fún ibi sì ni ìmọ̀.’ ”