Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 28:12-21 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Ṣugbọn níbo ni a ti lè rí ọgbọ́n?Níbo sì ni ìmọ̀ wà?

13. “Ẹnikẹ́ni kò mọ ọ̀nà ibi tí ó wà;bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ilẹ̀ alààyè.

14. Ibú sọ pé, ‘Kò sí ninu mi,’òkun sì ní, ‘Kò sí lọ́dọ̀ mi.’

15. Wúrà iyebíye kò lè rà á,fadaka kò sì ṣe é díwọ̀n iye rẹ̀.

16. A kò lè fi wúrà Ofiri díwọ̀n iye rẹ̀,tabi òkúta onikisi tabi safire tí wọ́n jẹ́ òkúta olówó iyebíye.

17. Ọgbọ́n níye lórí ju wúrà ati dígí lọ,a kò lè fi ohun ọ̀ṣọ́ tí a fi wúrà dáradára ṣe dípò rẹ̀.

18. Kí á má tilẹ̀ sọ ti iyùn tabi Kristali,ọgbọ́n ní iye lórí ju òkúta Pali lọ.

19. A kò lè fi wé òkúta topasi láti ilẹ̀ Etiopia,tabi kí á fi ojúlówó wúrà rà á.

20. “Níbo ni ọgbọ́n ti ń wá;níbo sì ni ìmọ̀ wà?

21. Ó pamọ́ lójú gbogbo ẹ̀dá alààyè,ati lójú àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run.

Ka pipe ipin Jobu 28