Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 22:1-14 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Elifasi ará Temani bá dáhùn pé,

2. “Ǹjẹ́ eniyan lè wúlò fún Ọlọrun?Nítòótọ́, bí eniyan tilẹ̀ jẹ́ ọlọ́gbọ́n, ara rẹ̀ ni ó wúlò fún.

3. Ǹjẹ́ jíjẹ́ olódodo rẹ̀ ṣe ohun rere kan fún Olodumare,tabi kí ni èrè rẹ̀ bí ó bá jẹ́ ẹni pípé?

4. Ṣé nítorí pé o bẹ̀rù rẹ̀ ni ó ṣe bá ọ wí,tí ó sì ń dá ọ lẹ́jọ́?

5. Ṣebí ìwà ibi rẹ ló pọ̀;tí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lópin?

6. O gba nǹkan ìdógò lọ́wọ́ àwọn arakunrin rẹ láìnídìí,O bọ́ wọn sí ìhòòhò goloto.

7. O kò fún aláàárẹ̀ ní omi mu,o kọ̀ láti fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ.

8. Ẹni tí ó lágbára gba ilẹ̀,ẹni tí ó lọ́lá sì ń gbé inú rẹ̀.

9. O lé àwọn opó jáde lọ́wọ́ òfo,o sì ṣẹ́ aláìní baba lápá.

10. Nítorí náà ni okùn dídẹ fi yí ọ ká,tí jìnnìjìnnì sì bò ọ́ lójijì.

11. Ìmọ́lẹ̀ rẹ ti di òkùnkùn, o kò ríran,ìgbì omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.

12. “Ṣebí Ọlọrun wà lókè ọ̀runÓ ń wo àwọn ìràwọ̀ nísàlẹ̀àní àwọn tí wọ́n ga jùlọ,bí ó ti wù kí wọ́n ga tó!

13. Sibẹsibẹ ò ń bèèrè pé, ‘Kí ni Ọlọrun mọ̀?’Ṣé ó lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn biribiri?

14. Ìkùukùu tí ó nípọn yí i ká,tóbẹ́ẹ̀ tí kò lè ríran,ó sì ń rìn ní òfuurufú ojú ọ̀run.

Ka pipe ipin Jobu 22