Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 21:9-22 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Kò sí ìfòyà ninu ilé wọn,bẹ́ẹ̀ ni Ọlọrun kò jẹ wọ́n níyà.

10. Àwọn mààlúù wọn ń gùn,wọ́n sì ń bímọ ní àbíyè.

11. Wọn a máa kó àwọn ọmọ wọn jáde bí agbo ẹran,àwọn ọmọ wọn a sì máa ṣe àríyá.

12. Wọn a máa fi aro, ìlù, ati fèrè kọrin,wọn a sì máa yọ̀ sí ohùn dùùrù.

13. Wọn a máa gbé inú ọlá,wọn a sì máa kú ikú alaafia.

14. Wọ́n ń sọ fún Ọlọrun pé, ‘Fi wá sílẹ̀!A kò fẹ́ mọ òfin rẹ.

15. Ta ni Olodumare, tí a óo fi máa sìn ín?Èrè wo ni ó wà níbẹ̀ fún wa bí à ń gbadura sí i?’

16. Wọ́n rò pé ìkáwọ́ wọn ni ọlà wọn wà,nítèmi n kò lè tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn eniyan burúkú.

17. “Ìgbà mélòó ni à ń pa fìtílà ẹni ibi?Ìgbà mélòó ni iṣẹ́ ibi wọn ń dà lé wọn lórí?Tabi tí Ọlọrun ṣe ìpín wọn ní ìrora ninu ibinu rẹ̀?

18. Ìgbà mélòó ni wọ́n dàbí àgékù koríko,tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ kiri,tabi bí ìyàngbò tí ìjì ń gbé lọ?

19. “O ní, ‘Ọlọrun ń to àìdára wọn jọ de àwọn ọmọ wọn.’Jẹ́ kí ó dà á lé wọn lórí, kí wọ́n baà lè mọ ohun tí wọ́n ṣe.

20. Jẹ́ kí wọ́n fi ojú ara wọn rí ìparun ara wọn,kí wọ́n sì rí ibinu Olodumare.

21. Kí ni ó kàn wọ́n pẹlu ilé wọn mọ́, lẹ́yìn tí wọn bá ti kú,nígbà tí a bá ti ké ọjọ́ wọn kúrò lórí ilẹ̀.

22. Ṣé ẹnìkan lè kọ́ Ọlọrun ní ìmọ̀,nígbà tí ó jẹ́ pé òun ni onídàájọ́ àwọn tí wọ́n wà ní ibi gíga?

Ka pipe ipin Jobu 21