29. Ṣé ẹ kò tíì bèèrè ọ̀nà lọ́wọ́ àwọn arìnrìnàjò?Ṣé ẹ kò sì tíì gba ẹ̀rí wọn, pé,
30. a dá ẹni ibi sí ní ọjọ́ ìdàrúdàpọ̀,ati pé a gbà á là ní ọjọ́ ibinu?
31. Kò sẹ́ni tó jẹ́ fẹ̀sùn kan ẹni ibi lójú rẹ̀,tabi kí ó gbẹ̀san nǹkan burúkú tí ó ṣe.
32. Nígbà tí a bá gbé e lọ sí itẹ́,àwọn olùṣọ́ a máa ṣọ́ ibojì rẹ̀.
33. Ẹgbẹẹgbẹrun èrò a tẹ̀lé e lọ sí ibojì,àìmọye eniyan a sì sin òkú rẹ̀;kódà, ilẹ̀ á dẹ̀ fún un ní ibojì rẹ̀.
34. Nítorí náà, kí ni ìsọkúsọ tí ẹ lè fi tù mí ninu?Kò sóhun tó kù ninu ọ̀rọ̀ yín,tó ju irọ́ lọ.”