Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 21:23-34 BIBELI MIMỌ (BM)

23. Ẹnìkan kú ninu ọpọlọpọ ọrọ̀,nítorí pé ó wà ninu ìdẹ̀ra ati àìfòyà,

24. ara rẹ̀ ń dán fún sísanra,ara sì tù ú dé mùdùnmúdùn.

25. Ẹlòmíràn kú pẹlu ìbànújẹ́ ọkàn,láìtọ́ ohun rere kankan wò rí.

26. Bákan náà ni gbogbo wọn ṣe sùn ninu erùpẹ̀,tí ìdin sì bò wọ́n.

27. “Wò ó! Mo mọ èrò ọkàn yín,mo sì mọ ète tí ẹ ní sí mi láti ṣe mí níbi.

28. Nítorí ẹ wí pé, ‘Níbo ni ilé àwọn eniyan ńlá wà;níbo sì ni àgọ́ àwọn aṣebi wà?’

29. Ṣé ẹ kò tíì bèèrè ọ̀nà lọ́wọ́ àwọn arìnrìnàjò?Ṣé ẹ kò sì tíì gba ẹ̀rí wọn, pé,

30. a dá ẹni ibi sí ní ọjọ́ ìdàrúdàpọ̀,ati pé a gbà á là ní ọjọ́ ibinu?

31. Kò sẹ́ni tó jẹ́ fẹ̀sùn kan ẹni ibi lójú rẹ̀,tabi kí ó gbẹ̀san nǹkan burúkú tí ó ṣe.

32. Nígbà tí a bá gbé e lọ sí itẹ́,àwọn olùṣọ́ a máa ṣọ́ ibojì rẹ̀.

33. Ẹgbẹẹgbẹrun èrò a tẹ̀lé e lọ sí ibojì,àìmọye eniyan a sì sin òkú rẹ̀;kódà, ilẹ̀ á dẹ̀ fún un ní ibojì rẹ̀.

34. Nítorí náà, kí ni ìsọkúsọ tí ẹ lè fi tù mí ninu?Kò sóhun tó kù ninu ọ̀rọ̀ yín,tó ju irọ́ lọ.”

Ka pipe ipin Jobu 21