Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 21:1-19 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Jobu dáhùn pé,

2. “Ẹ fetí sí ọ̀rọ̀ mi dáradára,kí ẹ sì jẹ́ kí ó jẹ́ ìtùnú fun yín.

3. Ẹ farabalẹ̀, kí ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,lẹ́yìn náà, ẹ lè máa fi mí ṣẹ̀sín ǹṣó.

4. Ṣé eniyan ni mò ń bá rojọ́ ni?Kí ló dé tí n óo fi mú sùúrù?

5. Ẹ wò mí, kí ẹnu yà yín,kí ẹ sì fọwọ́ bo ẹnu.

6. Nígbà tí mo ro ohun tí ó dé bá mi,ẹ̀rù bà mí, mo sì wárìrì.

7. Kí ló dé tí eniyan burúkú fi wà láàyè,tí ó di arúgbó, tí ó sì di alágbára?

8. Àwọn ọmọ wọn ati arọmọdọmọ wọndi eniyan pataki pataki lójú ayé wọn.

9. Kò sí ìfòyà ninu ilé wọn,bẹ́ẹ̀ ni Ọlọrun kò jẹ wọ́n níyà.

10. Àwọn mààlúù wọn ń gùn,wọ́n sì ń bímọ ní àbíyè.

11. Wọn a máa kó àwọn ọmọ wọn jáde bí agbo ẹran,àwọn ọmọ wọn a sì máa ṣe àríyá.

12. Wọn a máa fi aro, ìlù, ati fèrè kọrin,wọn a sì máa yọ̀ sí ohùn dùùrù.

13. Wọn a máa gbé inú ọlá,wọn a sì máa kú ikú alaafia.

14. Wọ́n ń sọ fún Ọlọrun pé, ‘Fi wá sílẹ̀!A kò fẹ́ mọ òfin rẹ.

15. Ta ni Olodumare, tí a óo fi máa sìn ín?Èrè wo ni ó wà níbẹ̀ fún wa bí à ń gbadura sí i?’

16. Wọ́n rò pé ìkáwọ́ wọn ni ọlà wọn wà,nítèmi n kò lè tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn eniyan burúkú.

17. “Ìgbà mélòó ni à ń pa fìtílà ẹni ibi?Ìgbà mélòó ni iṣẹ́ ibi wọn ń dà lé wọn lórí?Tabi tí Ọlọrun ṣe ìpín wọn ní ìrora ninu ibinu rẹ̀?

18. Ìgbà mélòó ni wọ́n dàbí àgékù koríko,tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ kiri,tabi bí ìyàngbò tí ìjì ń gbé lọ?

19. “O ní, ‘Ọlọrun ń to àìdára wọn jọ de àwọn ọmọ wọn.’Jẹ́ kí ó dà á lé wọn lórí, kí wọ́n baà lè mọ ohun tí wọ́n ṣe.

Ka pipe ipin Jobu 21