Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 18:1-15 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Bilidadi ará Ṣuha bá tún dáhùn pé,

2. “Ìgbàwo ni o óo sinmi ẹjọ́ tí ò ń tò yìí?Ohun tí a tí ń bá ọ sọ ni kí o gbé yẹ̀wò,kí á lè sọ èyí tí a tún fẹ́ sọ.

3. Kí ló dé tí o fi kà wá sí ẹranko,tí a di òmùgọ̀ lójú rẹ?

4. Ìwọ tí o faraya nítorí inú ń bí ọ,ṣé kí á sá kúrò láyé nítorí rẹ ni,tabi kí á ṣí àwọn àpáta nípò pada?

5. “Nítòótọ́, a ti pa fìtílà ẹni ibi,ahọ́n iná rẹ̀ kò sì mọ́lẹ̀ mọ́.

6. Inú àgọ́ rẹ̀ ṣókùnkùn,a sì ti pa àtùpà ìgbèrí rẹ̀.

7. Agbára rẹ̀ ti dín kù,ète rẹ̀ sì gbé e ṣubú.

8. Ó ti ẹsẹ̀ ara rẹ̀ bọ àwọ̀n,ó ń rìn lórí ọ̀fìn.

9. Tàkúté ti mú un ní gìgísẹ̀,ó ti kó sinu pańpẹ́.

10. A dẹ okùn sílẹ̀ fún un,a sì dẹ pańpẹ́ sí ojú ọ̀nà rẹ̀.

11. “Ìbẹ̀rù yí i ká,wọ́n ń lé e kiri.

12. Ebi pa agbára mọ́ ọn ninu,ìṣòro sì ti ṣetán láti gbé e ṣubú.

13. Àìsàn burúkú jẹ awọ ara rẹ̀,àkọ́bí ikú jẹ ẹ́ tọwọ́ tẹsẹ̀.

14. A fipá wọ́ ọ kúrò ninu àgọ́ rẹ̀ tí ó gbẹ́kẹ̀lé,a sì mú un lọ sọ́dọ̀ Ọba Ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀.

15. Àgọ́ rẹ̀ kún fún àwọn tí kì í ṣe tirẹ̀,imí-ọjọ́ fọ́nká sí gbogbo ibùgbé rẹ̀.

Ka pipe ipin Jobu 18