Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 15:5-13 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni ó ń fa irú ọ̀rọ̀ tí ń ti ẹnu rẹ jáde,ètè rẹ sì kún fún àrékérekè.

6. Ẹnu rẹ ni ó dá ọ lẹ́bi, kì í ṣe èmi;ẹ̀rí tí ò ń jẹ́ nípa rẹ ní ń ta kò ọ́.

7. “Ṣé ìwọ ni ẹni kinni tí wọ́n kọ́ bí láyé?Tabi o ṣàgbà àwọn òkè?

8. Ṣé o wà ninu ìgbìmọ̀ Ọlọrun?Tabi ìwọ nìkan ni o rò pé o gbọ́n?

9. Kí ni o mọ̀, tí àwa náà kò mọ̀?Òye kí ni o ní, tí ó jẹ́ ohun ìpamọ́ fún àwa?

10. Àwọn tí wọ́n hu ewú lórí wà láàrin wa, ati àwọn àgbàlagbà,àwọn tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.

11. Ṣé ìtùnú Ọlọrun kò tó fún ọ ni,àní ọ̀rọ̀ jẹ́ẹ́jẹ́ tí ó ń sọ fún ọ?

12. Àgbéré kí lò ń ṣe,tí o sì ń fi ojú burúkú wò wá.

13. Tí ọkàn rẹ yipada kúrò lọ́dọ̀ Ọlọrun,tí ò ń jẹ́ kí irú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ ti ẹnu rẹ jáde?

Ka pipe ipin Jobu 15