Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 15:12-28 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Àgbéré kí lò ń ṣe,tí o sì ń fi ojú burúkú wò wá.

13. Tí ọkàn rẹ yipada kúrò lọ́dọ̀ Ọlọrun,tí ò ń jẹ́ kí irú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ ti ẹnu rẹ jáde?

14. Kí ni eniyan jẹ́, tí ó fi lè mọ́ níwájú Ọlọrun?Kí ni ẹnikẹ́ni tí obinrin bí já mọ́, tí ó fi lè jẹ́ olódodo?

15. Wò ó, Ọlọrun kò fọkàn tán àwọn angẹli,àwọn ọ̀run kò sì mọ́ níwájú rẹ̀.

16. Kí á má tilẹ̀ wá sọ ti eniyantí ó jẹ́ aláìmọ́ ati ẹlẹ́gbin,tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bí ẹni mu omi!

17. “Fetí sílẹ̀, n óo sọ fún ọ,n óo sọ ohun tí ojú mi rí,

18. (ohun tí àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n sọ,tí àwọn baba wọn kò sì fi pamọ́,

19. àwọn nìkan ni a fún ní ilẹ̀ náà,àlejò kankan kò sì sí láàrin wọn).

20. Ẹni ibi ń yí ninu ìrora ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀,àní, ní gbogbo ọdún tí a là sílẹ̀ fún ìkà.

21. Etí rẹ̀ kún fún igbe tí ó bani lẹ́rù,ninu ìdẹ̀ra rẹ̀ àwọn apanirun yóo dìde sí i.

22. Kò gbàgbọ́ pé òun lè jáde kúrò ninu òkùnkùn;ati pé dájú, ikú idà ni yóo pa òun.

23. Ó ń wá oúnjẹ káàkiri, ó ń bèèrè pé,‘Níbo ló wà?’Òun gan-an sì nìyí, oúnjẹ àwọn igún!Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn ti súnmọ́ tòsí.

24. Ìdààmú ati ìrora dẹ́rùbà á,wọ́n ṣẹgun rẹ̀, bí ọba tí ó múra ogun.

25. Nítorí pé ó ṣíwọ́ sókè sí Ọlọrun,o sì ṣe oríkunkun sí Olodumare,

26. ó ń ṣe oríkunkun sí i,ó sì gbé apata tí ó nípọn lọ́wọ́ láti bá a jà;

27. nítorí pé ó sanra tóbẹ́ẹ̀ tí ojú rẹ̀ yíbò,ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ sì jẹ́ kìkì ọ̀rá.

28. Ó ń gbé ìlú tí ó ti di ahoro,ninu àwọn ilé tí eniyan kò gbọdọ̀ gbé,àwọn ilé tí yóo pada di òkítì àlàpà.

Ka pipe ipin Jobu 15