Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 10:5-18 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Ǹjẹ́ bí ọjọ́ ti eniyan ni ọjọ́ rẹ rí?Ǹjẹ́ ọdún rẹ rí bíi ti eniyan?

6. Tí o fi wá ń wádìí àṣìṣe mi,tí o sì ń tanná wá ẹ̀ṣẹ̀ mi?

7. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o mọ̀ pé n kò lẹ́bi,ati pé kò sí ẹnikẹ́nití ó lè gbà mí lọ́wọ́ rẹ.

8. Ọwọ́ rẹ ni o fi dá mi,ọwọ́ kan náà ni o sì tún fẹ́ fi pa mí run.

9. Ranti pé, amọ̀ ni o fi mọ mí,ṣé o tún fẹ́ sọ mí di erùpẹ̀ pada ni?

10. Ṣebí ìwọ ni o dà mí bí omi wàrà,tí o sì ṣù mí pọ̀ bíi wàrà sísè?

11. Ìwọ ni o fi awọ ati ẹran bò mí,tí o rán egungun ati iṣan mi pọ̀.

12. O fún mi ní ìyè,o sì fi ìfẹ́ ńlá rẹ tí kì í yẹ̀ hàn sí mi,ìtọ́jú rẹ sì ti gbé ẹ̀mí mi ró.

13. Sibẹ o pa gbogbo nǹkan wọnyi mọ́ sọ́kàn rẹ,mo mọ̀ pé èrò ọkàn rẹ ni pé,

14. bí mo bá ṣẹ̀, o óo dójú lé mi,o kò ní jẹ́ kí n lọ láìjìyà.

15. Bí mo bá ṣe àìdára, mo gbé,ṣugbọn bí mo ṣe dáradára, n kò lè yangàn,nítorí ìbànújẹ́ ati ìtìjú bò mí mọ́lẹ̀.

16. Bí mo bá ṣe àṣeyọrí,o óo máa lépa mi bíi kinniun;ò ń lo agbára rẹ láti pa mí lára.

17. O wá àwọn ẹlẹ́rìí tuntun pé kí wọ́n dojú kọ mí,O tún bẹ̀rẹ̀ sí bínú sí mi lọpọlọpọ,O mú kí ogun mìíràn dó tì mí.

18. “Kí ló dé tí o fi mú mi jáde láti inú ìyá mi?Ìbá sàn kí n ti kú,kí ẹnikẹ́ni tó rí mi.

Ka pipe ipin Jobu 10