Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 51:38-53 BIBELI MIMỌ (BM)

38. Gbogbo wọn yóo bú papọ̀ bíi kinniun,wọn yóo sì ké bí àwọn ọmọ kinniun.

39. Nígbà tí ara wọn bá gbóná,n óo se àsè kan fún wọn.N óo rọ wọ́n lọ́tí yó,títí tí wọn óo fi máa yọ ayọ̀ ẹ̀sín,tí wọn óo sì sùn lọ títí ayé.Wọn óo sùn, wọn kò sì ní jí mọ́.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

40. N óo fà wọ́n lọ sí ibi tí wọn tí ń pa ẹran,bí ọ̀dọ́ aguntan, ati àgbò ati òbúkọ.”

41. OLUWA ní,“Ẹ wò ó bí ogun ti kó Babiloni,Babiloni tí gbogbo ayé ń pọ́nlé!Ó wá di àríbẹ̀rù láàrin àwọn orílẹ̀-èdè!

42. Òkun ti ru bo Babiloni mọ́lẹ̀.Ìgbì òkun ti bò ó mọ́lẹ̀.

43. Àwọn ìlú rẹ̀ ti di àríbẹ̀rù,wọ́n ti di ilẹ̀ gbígbẹ ati aṣálẹ̀,ilẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé mọ́,tí ọmọ eniyan kò sì gbà kọjá mọ́.

44. N óo fìyà jẹ oriṣa Bẹli ní Babiloni,n óo jẹ́ kí ó pọ ohun tí ó gbé mì.Àwọn orílẹ̀-èdè kò ní lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ mọ́,odi Babiloni pàápàá yóo wó lulẹ̀.

45. “Ẹ̀yin eniyan mi, ẹ jáde kúrò níbẹ̀!Kí olukuluku sá àsálà, kúrò lọ́wọ́ ibinu gbígbóná OLUWA!

46. Ẹ mọ́kàn, ẹ má bẹ̀rù,nítorí ìròyìn tí ẹ̀ ń gbọ́ nípa ilẹ̀ náà,nígbà tí ẹ bá gbọ́ ìròyìn kan ní ọdún yìí,tí ẹ tún gbọ́ òmíràn ní ọdún tí ń bọ̀,tí ìwà ipá sì wà ní ilẹ̀ náà,tí àwọn ìjòyè sì ń dojú ìjà kọ ara wọn.

47. Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀tí n óo fìyà jẹ àwọn ère ilẹ̀ Babiloni.Ojú yóo ti gbogbo ilẹ̀ rẹ̀,òkú àwọn eniyan rẹ̀ tí ogun yóo pa,yóo wà nílẹ̀ káàkiri ìgboro.

48. Nítorí náà, ọ̀run ati ayé, ati gbogbo ohun tí ó wà ninu wọn,yóo yọ̀ nítorí ìṣubú Babiloni,nítorí pé apanirun yóo wá gbógun tì í, láti ìhà àríwá,Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

49. Bí àwọn tí ogun Babiloni pa ní àwọn orílẹ̀-èdè ayé,ti ṣubú níwájú rẹ̀.Bẹ́ẹ̀ ni Babiloni náà gbọdọ̀ ṣubú,nítorí àwọn tí wọ́n pa ní Israẹli.”

50. OLUWA sọ fún àwọn eniyan rẹ̀ ní Babiloni pé,“Ẹ̀yin tí ẹ bọ́ lọ́wọ́ idà,ẹ má dúró, ẹ máa sálọ!Ẹ ranti OLUWA ní ilẹ̀ òkèèrè,kí ẹ sì máa ronú nípa Jerusalẹmu pẹlu.

51. Ẹ̀ ń sọ pé ojú ń tì yín nítorí pé wọ́n kẹ́gàn yín;ẹ ní ìtìjú dà bò yín,nítorí pé àwọn àjèjì ti wọ ibi mímọ́ ilé OLUWA.

52. Nítorí náà, èmi OLUWA ń sọ nisinsinyii pé,ọjọ́ ń bọ̀, tí n óo ṣe ìdájọ́ lórí àwọn ère rẹ̀;àwọn tí wọ́n fara gbọgbẹ́ yóo máa kérora,ní gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.

53. Bí Babiloni tilẹ̀ ga tí ó kan ojú ọ̀run,tí ó sì mọ odi yí àwọn ibi ààbò rẹ̀ gíga ká,sibẹsibẹ n óo rán apanirun sí i.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

Ka pipe ipin Jeremaya 51