Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 31:4-6 BIBELI MIMỌ (BM)

4. N óo tún yín gbé dìde, ẹ óo sì di ọ̀tun, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.Ẹ óo tún fi aro lu ìlù ayọ̀, ẹ óo sì jó ijó ìdùnnú.

5. Ẹ óo tún ṣe ọgbà àjàrà sórí òkè Samaria;àwọn tí wọ́n gbin àjàrà ni yóo sì gbádùn èso orí rẹ̀.

6. Nítorí pé ọjọ́ kan ń bọ̀, tí àwọn aṣọ́nà yóo pè yín láti orí òkè Efuraimu pé,‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí á lọ sí òkè Sioni,sí ọ̀dọ̀ OLUWA Ọlọrun wa.’ ”

Ka pipe ipin Jeremaya 31