Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 20:11-18 BIBELI MIMỌ (BM)

11. Ṣugbọn OLUWA wà pẹlu mi bíi jagunjagun tí ó bani lẹ́rù.Nítorí náà àwọn tí wọn ń lépa mi yóo kọsẹ̀,apá wọn kò ní ká mi.Ojú yóo tì wọ́n lọpọlọpọ nítorí wọn kò ní lè borí mi.Ẹ̀sín tí ẹnikẹ́ni kò ní gbàgbé yóo dé bá wọn títí lae.

12. OLUWA àwọn ọmọ ogun, ìwọ tíí dán olódodo wò,ìwọ tí o mọ ọkàn ati èrò eniyan.Gbẹ̀san lára wọn kí n fojú rí i,nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.

13. Ẹ kọrin sí OLUWA,ẹ yin OLUWA.Nítorí pé ó gba ẹ̀mí aláìní sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn aṣebi.

14. Ègún ni fún ọjọ́ tí a bí mi,kí ọjọ́ tí ìyá mi bí mi má jẹ́ ọjọ́ ayọ̀.

15. Ègún ni fún ẹni tí ó yọ̀ fún baba mi,tí ó sọ fún un pé,“Iyawo rẹ ti bí ọmọkunrin kan fún ọ,tí ó mú inú rẹ̀ dùn.”

16. Kí olúwarẹ̀ dàbí àwọn ìlú tí OLUWA parun láìṣàánú wọn.Kí ó gbọ́ igbe lówùúrọ̀,ati ariwo ìdágìrì lọ́sàn-án gangan.

17. Nítorí pé kò pa mí ninu oyún,kí inú ìyá mi lè jẹ́ isà òkú fún mi.Kí n wà ninu oyún ninu ìyá mi títí ayé.

18. Kí ló dé tí wọn bí mi sáyé?Ṣé kí n lè máa fojú rí ìṣẹ́ ati ìbànújẹ́ ni?Kí gbogbo ọjọ́ ayé mi lè kún fún ìtìjú?

Ka pipe ipin Jeremaya 20