Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 18:7-14 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Bí mo bá sọ pé n óo fa orílẹ̀-èdè kan, tabi ìjọba kan tu, n óo wó o lulẹ̀, n óo sì pa á run,

8. bí orílẹ̀-èdè ọ̀hún bá yipada kúrò ninu ìwà burúkú rẹ̀, n óo dá ibi tí mo ti fẹ́ ṣe sí i tẹ́lẹ̀ dúró.

9. Bí mo bá sọ pé n óo gbé orílẹ̀-èdè kan dìde, n óo sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀;

10. bí ó bá ṣe nǹkan burúkú lójú mi, tí kò gbọ́ràn sí mi lẹ́nu, n óo dá nǹkan rere tí mo ti fẹ́ ṣe fún un dúró.

11. Nítorí náà, sọ fún àwọn ará Juda ati àwọn tí wọn ń gbé Jerusalẹmu pé, èmi OLUWA ní, mò ń pète ibi kan si yín, mo sì ń pinnu rẹ̀ lọ́wọ́ báyìí, kí olukuluku yín yipada kúrò ninu ibi tí ó ń ṣe; kí ẹ sì tún ìwà ati ìṣe yín ṣe.

12. Ṣugbọn wọ́n ń wí pé, ‘Rárá o, OLUWA kàn ń sọ tirẹ̀ ni, tinú wa ni a óo ṣe, olukuluku yóo máa lo agídí ọkàn rẹ̀.’ ”

13. Nítorí náà OLUWA ní,“Ẹ bèèrè láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè,bí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ irú rẹ̀ rí.Israẹli ti ṣe ohun tó burú gan-an.

14. Ṣé yìnyín òkè Lẹbanoni a máa dà ní pàlàpálá Sirioni?Àbí omi tútù tí máa ń ṣàn láti inú òkè rẹ̀ a máa gbẹ?

Ka pipe ipin Jeremaya 18