Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 17:13-23 BIBELI MIMỌ (BM)

13. OLUWA, ìwọ ni Israẹli gbójú lé,ojú yóo ti gbogbo àwọn tí wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀.A óo kọ orúkọ àwọn tí wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀ sórí ilẹ̀,yóo sì parẹ́,nítorí pé wọ́n ti kọ OLUWA, orísun omi ìyè, sílẹ̀.

14. Wò mí sàn, OLUWA, ara mi yóo sì dá,gbà mí, n óo sì bọ́ ninu ewu.Nítorí pé ìwọ ni mò ń yìn.

15. Wò ó! Wọ́n ń bi mí pé,“Níbo ni gbogbo ìhàlẹ̀ OLUWA já sí?Jẹ́ kí ó ṣẹ, kí á rí i!”

16. N kò bẹ̀bẹ̀ pé kí o rán ibi sí wọn,bẹ́ẹ̀ ni n kò fẹ́ ọjọ́ ibi fún wọn.OLUWA, o mọ̀ bẹ́ẹ̀.Ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde kò tún lè ṣàjèjì sí ọ.

17. Má di ohun ẹ̀rù fún mi,nítorí ìwọ ni ibi ààbò mi ní ọjọ́ ibi.

18. Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn tí wọn ń ṣe inúnibíni mi,ṣugbọn kí ojú má tì mí.Jẹ́ kí ìpayà bá wọn,ṣugbọn má jẹ́ kí èmi páyà.Mú ọjọ́ ibi dé bá wọn; pa wọ́n run ní àpatúnpa.

19. OLUWA sọ fún mi pé, “Lọ dúró ní ẹnubodè Bẹnjamini níbí, tí àwọn ọba Juda máa ń gbà wọlé, tí wọn sìí gbà jáde; ati ní gbogbo ẹnubodè Jerusalẹmu,

20. kí o wí pé, ‘Ẹ gbọ́ bí OLUWA ti wí, ẹ̀yin ọba Juda, ati gbogbo ẹ̀yin ará Juda ati gbogbo ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé Jerusalẹmu, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gba ẹnu ọ̀nà wọnyi wọlé.

21. OLUWA ní kí ẹ ṣọ́ra fún ẹ̀mí yín, ẹ má máa ru ẹrù ní ọjọ́ ìsinmi, ẹ má gbé ẹrù wọ ẹnubodè Jerusalẹmu ní ọjọ́ ìsinmi mọ́.

22. Ẹ kò gbọdọ̀ ru ẹrù jáde ní ilé yín ní ọjọ́ ìsinmi. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan, ẹ níláti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, bí mo ti pa á láṣẹ fún àwọn baba ńlá yín.

23. Sibẹ àwọn baba yín kò gbọ́; wọn kò sì fetí sílẹ̀, wọ́n ṣe oríkunkun, kí wọn má baà gbọ́, kí wọn má baà gba ìtọ́ni.

Ka pipe ipin Jeremaya 17