Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹnẹsisi 9:23-29 BIBELI MIMỌ (BM)

23. Ṣemu ati Jafẹti bá mú aṣọ kan, wọ́n fà á kọ́ èjìká wọn, wọ́n fi ẹ̀yìn rìn lọ sí ibi tí baba wọn sùn sí, wọ́n sì dà á bò ó, wọ́n kọ ojú sí ẹ̀gbẹ́ kan, wọn kò sì rí ìhòòhò baba wọn.

24. Nígbà tí ọtí dá lójú Noa, tí ó gbọ́ ohun tí àbíkẹ́yìn rẹ̀ ṣe sí i,

25. Ó ní,“Ẹni ègún ni Kenaani,ẹrú lásánlàsàn ni yóo jẹ́ fún àwọn arakunrin rẹ̀.”

26. Ó tún fi kún un pé,“Kí OLUWA Ọlọrun mi bukun Ṣemu,ẹrú rẹ̀ ni Kenaani yóo máa ṣe.

27. Kí Ọlọrun sọ ìdílé Jafẹti di pupọ,kí ó máa gbé ninu àgọ́ Ṣemu,ẹrú rẹ̀ ni Kenaani yóo máa ṣe.”

28. Ọọdunrun ọdún ó lé aadọta (350) ni Noa tún gbé sí i lẹ́yìn ìkún omi.

29. Noa kú nígbà tí ó di ẹni ẹgbẹrun ọdún ó dín aadọta (950).

Ka pipe ipin Jẹnẹsisi 9