Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹnẹsisi 36:30-43 BIBELI MIMỌ (BM)

30. Diṣoni, Eseri, ati Diṣani. Àwọn ìjòyè ilẹ̀ Hori, gẹ́gẹ́ bí olórí ìdílé ìdílé wọn ní ilẹ̀ Seiri.

31. Àwọn ọba tí wọ́n jẹ ní ilẹ̀ Edomu kí ó tó di pé ẹnikẹ́ni jọba ní ilẹ̀ Israẹli nìwọ̀nyí:

32. Bela, ọmọ Beori jọba ní Edomu, orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.

33. Nígbà tí Bela kú, Jobabu, ọmọ Sera, ará Bosira gorí oyè.

34. Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu ti ilẹ̀ Temani, gorí oyè.

35. Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi, ọmọ Bedadi, tí ó ṣẹgun Midiani, ní ilẹ̀ Moabu gorí oyè, orúkọ ìlú tirẹ̀ ni Afiti.

36. Nígbà tí Hadadi kú, Samila ti Masireka gorí oyè.

37. Nígbà tí Samila kú, Ṣaulu ará Rehoboti lẹ́bàá odò Yufurate gorí oyè.

38. Nígbà tí Ṣaulu kú, Baali Hanani, ọmọ Akibori gorí oyè.

39. Nígbà tí Baali Hanani ọmọ Akibori kú, Hadadi gorí oyè, orúkọ ìlú tirẹ̀ ni Pau, orúkọ aya rẹ̀ ni Mehetabeli, ọmọ Matiredi, ọmọbinrin Mesahabu.

40. Orúkọ àwọn ìjòyè tí wọ́n ṣẹ̀ lára Esau nìwọ̀nyí, gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn ati ìlú tí olukuluku ti jọba: Timna, Alfa, Jeteti,

41. Oholibama, Ela, Pinoni,

42. Kenasi, Temani, Mibisari,

43. Magidieli ati Iramu. Àwọn ni ìjòyè ní Edomu, gẹ́gẹ́ bí ìlú wọn ní ilẹ̀ ìní wọn, Esau tí àdàpè rẹ̀ ń jẹ́ Edomu sì ni baba àwọn ará Edomu.

Ka pipe ipin Jẹnẹsisi 36