Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹnẹsisi 21:28-31 BIBELI MIMỌ (BM)

28. Abrahamu ya abo ọmọ aguntan meje ninu agbo rẹ̀ sọ́tọ̀.

29. Abimeleki bá bi Abrahamu, ó ní, “Kí ni ìtumọ̀ abo ọmọ aguntan meje tí o yà sọ́tọ̀ wọnyi?”

30. Abrahamu dá a lóhùn pé, “Gba abo ọmọ aguntan meje wọnyi lọ́wọ́ mi, kí o lè jẹ́ ẹlẹ́rìí mi pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”

31. Ìdí rẹ̀ nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní Beeriṣeba, nítorí pé níbẹ̀ ni àwọn mejeeji ti búra.

Ka pipe ipin Jẹnẹsisi 21